YORUBA NI ÈYÀ TÍ Ó NÍ ÌGBÀGBÓ NÍNÚ ÌṢÒKAN NÀÌJÍRÍÀ JÙ NÍ ORÍLÈ-ÈDÈ YÌÍ....Sẹnetọ Anthony Adefuye

    Sẹnetọ Anthony Adefuye ni akọwe agba fun ẹgbẹ Iṣọkan ,ile Yoruba.Lẹnu kope-kope yii ni awon akọròyìn ṣe abewo sì bàbá ọhun látàrí  isejoba dẹmokiresi tí ó ń lọ lọwọ nítorí bàbá naa jẹ ọkan gbòógì ninu àwọn tí ó já fún ìjọba dẹmokiresi ni orile-ede Naijiria.
     Nígbà tí bàbá Adefuye yíò bẹrẹ ọrọ ni ó kọkọ  fi ìdùnnú rẹ han si bi Ọlọ́run Eledumare ṣe pada fi ààyè gba aarẹ Bola Ahmad Tinubu gẹgẹ bi aarẹ ọmọ Yoruba àkókò tí ó jẹ ni orile-ede Naijiria lẹyin ọpọlọpọ ìdúróṣinṣin àti aforiti tí àwọn ọmọ Yoruba ti ni lati ìgbà tí orile-ede èdè Nàìjíríà tí gba ominira lọ́wọ́ ìjọba ológun. 
       Sẹnetọ Anthony ko sai mẹ́nu bá diẹ ninu ìṣòro tí ìjọba ológun da silẹ l'orílè-èdè Naijiria nígbà tí wón n ṣe àkóso,ṣùgbọ́n ju gbogbo rẹ lọ, wọn fii ọpẹ fún Eledua tí ó ti gba Nàìjíríà pada láti bi ọdún mẹẹẹdọgbọn seyin lọwọ Ológun.
          Wọn kò sàì ṣalaye wipe loootọ orile-ede Naijiria ko i tí de ibi ti gbogbo ọmọ Naijiria ni afojusun kí ó ti dé ní irú asikoyi ṣùgbọ́n wọn fi ìrètí wọn han wipe laipe yii a o de ibi tí a ń lò nítorí wipe diẹ diẹ ní 
       Ninu ifọrọwerọ yii, ni Sẹnetọ Anthony tí ṣalaye bi àwọn ẹ̀yà ọmọ Yoruba tí dúró ṣinṣin ninu ìgbàgbó wọn nípa Iṣọkan orile-ede Nàìjíríà tí wón sì kọ jalè láti lọ ní ilo tiwọn,  ni gbogbo ìgbà tí ẹ̀kọ ko ba ṣe bẹẹ ṣe ojú mímu ni orile-ede yii.
      Bàbá ni,  a ó rántí wípé ìgbà kan ni àwọn ẹ̀yà ibo da ẹgbẹ́ Biafira silẹ tí wón sì ń fi da orile-ede láàmú látàrí wipe won gbagbọ wipe eto ijoba alasepo yii ko bawọn lára mú
      Bakannaa, ọpọlọpọ ìgbà ni àwọn kan ti dìde ní ilé Haúsá tí wón n sọ ara won ni oriṣiiriṣii orúkọ,tí wón sì ń kọjú ija si awọn ẹ̀yà mìíràn bi ó tilè jẹ wipe awon ni wọn wa lori aleefa, tí ìní lára náà pọ to bẹẹ gẹẹ  fún ọmọ Yoruba láti ṣe ìpinnu pe ki olúkúlùkù kó ẹkọ ẹ  dání loootọ,ṣùgbọ́n, tí àwọn àgbàlagbà ilé Yorùbá,ma n fi gbogbo igba ,pẹ̀tù sí àwon ọmọ lẹyin wọn lọ́kàn ,pé kò sí ohun tí ó dára tó àlàáfíà àti Iṣọkan orile-ede Naijiria.
      Sẹnetọ Anthony, ko sàì fẹnu kan bí ìjọba àpapò ṣe ni làti fi kún owo oṣù àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba, kí ó bá le to wọn náà,wọn salaye wipe owo imú relé ni ipari oṣù gbọdọ jẹ owo ti o se gb'ale,tí ó lè bọ ìyàwó àti ọmọ, tí ó sì gbọdọ le rán ọmọ ni ile ìwé, ni eyii tí àwọn ko si ro wípé àádọ́rin naira lè ṣe rara.
    Wọn wípé,  ó ṣe pàtàkì láti tọju mẹkunnu tí ó bá ń ṣíṣe fún ni,nítorí ẹni tí èèyàn bá fún ni owo ti ko rerin,ó ti di dandan kí ó ṣe isé ti kọ rẹrin-in fún ni, ní èyí tí ko si ni jẹ ki orile-ede ṣe bẹẹ tẹ síwájú.
    Lákòótán, Sẹnetọ Adefuye wa pé àkíyèsí ìjọba àpapò sì ìlànà ìfinijoyè àti ìfinijoba kaakiri ilẹ̀ Yoruba,nítorí  àwọn ìwà tí kò yẹ kí a ba lọwọ ara ìlú, ni a má ń bá lọwọ àwọn ọba mìíràn ni ilé Yorùbá ni èyí tí ó sì ma n jẹ kí àwọn ènìyàn fẹ ma n fi ojú yẹpẹrẹ wo ipò Oríadè ilé Yorùbá. 
      

Comments

Popular posts from this blog

Ọmọlúwàbí Stakeholders Pay Courtesy Visit to Aregbesola, Reaffirm Loyalty to ADC Ideals

APC Chieftain Odukoya Adeyinka Sefiu Resigns, Cites Failed Promises and Unfair Treatment.

FROM BLACKOUT TO BRIGHT LIGHTS: How Dr. Naheem Balogun Rewrote Epe’s Story